Lamentations 3

1Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú
pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn
nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;
3Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí mi
síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

4Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó
ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká
pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,
bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

7Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;
ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,
ó kọ àdúrà mi.
9Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;
ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.

10Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,
bí i kìnnìún tí ó sápamọ́.
11Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀
ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12Ó fa ọfà rẹ̀ yọ
ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.

13Ó fa ọkàn mí ya
pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;
wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò
àti ìdààmú bí omi.

16Ó ti fi òkúta kán eyín mi;
ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;
mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ
àti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,
ìkorò àti ìbànújẹ́.
20Mo ṣèrántí wọn,
ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn
àti nítorí náà ní mo nírètí.

22Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,
nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;
títóbi ni òdodo rẹ̀.
24Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;
nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.

25Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,
sí àwọn tí ó ń wá a.
26Ó dára kí a ní sùúrù
fún ìgbàlà Olúwa.
27Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà
nígbà tí ó wà ní èwe.

28Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,
nítorí Olúwa ti fi fún un.
29Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—
ìrètí sì lè wà.
30Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,
sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.

31Ènìyàn kò di ìtanù
lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,
nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá
tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.

34Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀
gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀
níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ.
36Láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,
Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.

37Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀
tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ
ni rere àti búburú tí ń wá?
39Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn
nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?

40Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò,
kí a sì tọ Olúwa lọ.
41Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè
sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:
42“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀
ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.

43“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;
ìwọ ń parun láìsí àánú.
44Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ
pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn
láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

46“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn
gbòòrò sí wa.
47Àwa ti jìyà àti ìparun,
nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò
nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49Ojú mi kò dá fún omijé,
láì sinmi,
50títí ìgbà tí Olúwa yóò ṣíjú wolẹ̀
láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi
nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.

52Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí
dẹ mí bí ẹyẹ.
53Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò
wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54Orí mi kún fún omi,
mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.

55Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,
láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi: “Má ṣe di etí rẹ
sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,
o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”

58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,
o ra ẹ̀mí mi padà.
59O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi
Gbé ẹjọ́ mi ró!
60Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,
gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.

61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn
àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi—
62Ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ
sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,
wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.

64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn
fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,
kí o sì fi wọ́n ré.
66Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,
lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Copyright information for YorBMYO